Font Size
Isaiah 66:1-2
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Isaiah 66:1-2
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ìdájọ́ àti ìrètí
66 (A)Báyìí ni Olúwa wí:
“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,
ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,
Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?
Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
2 Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,
bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”
ni Olúwa wí.
“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:
ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,
tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.